22
Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àye ̀ ̣ wò Ènìyàn Àti Àwọn È ̣dá Abe ̀ ̣ mí Mìíràn Oyèbámijí, Akeem Ko ́ ̣ láwọlé Federal College of Education, Zaria 08035926490 [email protected] Àsamo ̣ ̀ Yorùbá bo ̀ ̣ wo ́ ̣ n ní ilé ni àá wò, kí á tó sọ ọmọ lórúkọ. Òwe yìí yóò máa to ́ ̣ ka sí o ̀ ̣ nà tí ìran Yorùbá máa ń gbà ronú kí wọn tó dáwo ́ ̣ le iṣe ́ ̣ tàbí nǹkan kan láti ṣe tàbí ìwà kan láti hù. Yorùbá ge ́ ̣ ge ́ ̣ bí e ̀ ̣ yà kan tàbí oríle ̀ ̣ -èdè kan je ́ ̣ aláròjinle ̀ ̣ , olùwádìí àti alákìyésìí. Lára ìwádìí àti àròjinle ̀ ̣ pe ̀ ̣ lú àkíyèsí wo ́ ̣ n ní pé kí Olódùmarè tó dá àwọn (ọmọ ènìyàn) ni ó ti ko ́ ̣ ko ́ ̣ dá àwon nǹkan kan sí àyíká wọn. Ìbéèrè ti wo ́ ̣ n ko ́ ̣ ko ́ ̣ ń bi ara wọn ni pé kí ni èrèdí dídá tí Olódùmarè ko ́ ̣ ko ́ ̣ dá àwọn nǹkan wo ̀ ̣ nyìí ṣaájú kí ó tó dà àwọn? Nínú àròjinle ̀ ̣ won nàá ni wo ́ ̣ n tí ń wá ìdáhùn pé Olódùmarè dá àwọn nǹkan wo ̀ ̣ nyìí fún ìlò àti àǹfààní ọmọnìyàn ni. Púpọ nínú àwọn nǹkan tí Olódùmarè dá sí àyíká e ̀ ̣ dà bíi afe ́ ̣ fe ́ ̣ , odò (omi), igbó kìjikìji, ewéko, òkè ńlánlá, àpáta, ẹranko ìgbẹ at̀i tilé, abbl ló je ́ ̣ pé Olódùmarè dá wọn fún ìlò ọmọ e ̀ ̣ dá ènìyàn. Nínú ìṣe ̀ ̣ mí ayé ọmọ e ̀ ̣ dá ènìyàn, igun pàtàkì ni Yorùbá fi o ̀ ̣ ro ̀ ̣ àlàáfìá àti ìlera wọn sí. Irú ọwo ́ ̣ wo ni àwọn ènìyàn fi mú o ̀ ̣ ro ̀ ̣ ilera won? Oju wo ni wo ́ ̣ n fi ń wo àwọn e ̀ ̣ àyíká tí wo ́ ̣ n kì í ṣe ènìyàn wo ̀ ̣ nyìí? Ǹje ́ ̣ àwọn ènìyàn àwùjọ mo ̀ ̣ pé bí a bá ń so ̀ ̣ ro ̀ ̣ ìlera tó péye, ohun tí a ń wá lọ sí sókótó ń bẹ ní àpò sòkòtò wa bí? Pépà yìí tan ìmo ́ ̣ le ̀ ̣ sí orísìrísìí o ̀ ̣ nà tí a le gbà ṣe àmúlò àwọn nǹkan tí Olódùmarè dà sí àyíká wà fún ìlera àti ìse ̀ ̣ mí ayé tó péye.

Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

Embed Size (px)

Citation preview

Page 1: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyewò Ènìyàn Àti Àwọn Edá Abemí Mìíràn

Oyèbámijí, Akeem Koláwọlé

Federal College of Education, Zaria 08035926490

[email protected]

Àsamo Yorùbá bo won ní ilé ni àá wò, kí á tó sọ ọmọ lórúkọ. Òwe yìí yóò máa toka sí onà tí ìran Yorùbá máa ń gbà ronú kí wọn tó dáwo le iṣe tàbí nǹkan kan láti ṣe tàbí ìwà kan láti hù. Yorùbá gege bí eyà kan tàbí oríle-èdè kan je aláròjinle, olùwádìí àti alákìyésìí. Lára ìwádìí àti àròjinle pelú àkíyèsí won ní pé kí Olódùmarè tó dá àwọn (ọmọ ènìyàn) ni ó ti koko dá àwon nǹkan kan sí àyíká wọn. Ìbéèrè ti won koko ń bi ara wọn ni pé kí ni èrèdí dídá tí Olódùmarè koko dá àwọn nǹkan wonyìí ṣaájú kí ó tó dà àwọn? Nínú àròjinle won nàá ni won tí ń wá ìdáhùn pé Olódùmarè dá àwọn nǹkan wonyìí fún ìlò àti àǹfààní ọmọnìyàn ni. Púpọ nínú àwọn nǹkan tí Olódùmarè dá sí àyíká edà bíi afefe, odò (omi), igbó kìjikìji, ewéko, òkè ńlánlá, àpáta, ẹranko ìgbẹ ati tilé, abbl ló je pé Olódùmarè dá wọn fún ìlò ọmọ edá ènìyàn. Nínú ìṣemí ayé ọmọ edá ènìyàn, igun pàtàkì ni Yorùbá fi oro àlàáfìá àti ìlera wọn sí. Irú ọwo wo ni àwọn ènìyàn fi mú oro ilera won? Oju wo ni won fi ń wo àwọn edá àyíká tí won kì í ṣe ènìyàn wonyìí? Ǹje àwọn ènìyàn àwùjọ mo pé bí a bá ń soro ìlera tó péye, ohun tí a ń wá lọ sí sókótó ń bẹ ní àpò sòkòtò wa bí? Pépà yìí tan ìmole sí orísìrísìí onà tí a le gbà ṣe àmúlò àwọn nǹkan tí Olódùmarè dà sí àyíká wà fún ìlera àti ìsemí ayé tó péye.

Page 2: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

86

Yorùbá: Journal of the Yorùbá Studies Association of Nigeria (Vol. 8 No. 2)

Ìfáárà: Kin ni Àyíká

Àyíká je gbogbo aayé tí ó súnmo tàbí tí ó wà ní ìtòsí ibi tí

ènìyàn ń gbé. Àwọn nǹkan àwòmo àyíká lè je ohun tí a lè fojú rí

tàbí fọwo kàn. Wọn tún lè je ohun àfinúrò tí ó ńii ṣe pelú

ìgbàgbo ẹnìkan pé àwọn emí tàbí edá kan tí a kò lè fojú rí tàbí

fọwo kàn wà ní àyíká wa. Yorùbá bo won ní ìlera lọro. Yorùbá a

tún máa sọ pé àlàáfìá ni olúborí oore tí Ọlorun Olódùmarè le ṣe

fún edá. Pé ẹni tí ó bá ti ní àlàáfìà, ohun gbogbo ló ní. Bí ó tile

je pé oríṣìíríṣìí onà ni a lè gbé oro nípa ìlera edá gbà, ìlera

ènìyàn tó níi ṣe pelú àwòmo àyíká ní pépà yìí fe fúnká mo.

Àfojúsùn pépà yìí ni pé nígbà tí ènìyàn bá ní àlàáfìà tó péye

nípa ṣíṣe àmúlò àwọn ohun tí Olódùmarè dá sí àyíká rẹ, tí àyíká

náà si tòrò nini, edá ènìyàn yóò lè sin Olódùmarè nípa fífi ọpe

fún un gege bí Ọba Adedàá Asedá àti Olùpèsè.

Irú ìwà yìí ni yóò jẹ kí inú Olódùmarè máa dùn kí inú

edá gbogbo náà si máa dùn pelú. Olódùmarè ni ó fi ènìyàn ṣe

olórí gbogbo àwọn edá tó dá (Bíbélì, Kùránì àti Ẹsẹ-ifá) toka sí

èyí, síbe ètò owó nílé lókò lódò ni àtìrandíran Yorùbá ti ń lo

saájú kí àwọn èèbó tó gòkè odò wá. Ìtumo owó nílé lóko lódò ni

pé àwọn edá yòókù yàto si ènìyàn ti Olódùmarè dá wonyìí ní

àwọn ètò tàbí àfojúsùn tí won ń retí lodo ènìyàn, bí ó tile je pé a

dá wọn láti le è wúlò fún ènìyàn nàà ni.

Gege bi àkòrí iṣe yìí, ‘ètò ìlera ajẹmo àyíká: àyewò

ìbáṣepo láàrín ènìyàn àti edá abemí mìíràn,’ oríṣìírìṣìí onà tí

ènìyàn le gbà ṣe àmúló àyíká tàbí lo ànfààní àwọn nǹkan tí

Olódùmarè dà sí àyíká re lonà tó to fún ìlera ni a ó máa fúnká

mo nínú pépà yìí. Kí iṣe àpilekọ yìí lè ní òòrìn, a ó tọpa re wọ

inú ìgbàgbo, esìn, èrò ìjìnle àti báyéṣerí àwọn Yorùbá. Díe nínú

Page 3: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

87

Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyewò Ènìyàn Àti Àwọn Edá Abemí Mìíràn

àwọn ohun tí Olódùmarè dá tí a ó máa ṣàlàyé gege bí wọn ṣe

wúlò fún ìlera ọmọ edá ènìyàn ní àyíká wọn ni afefe, odò/omi,

igi/ewéko, àpáta/òkè àti ẹranko lóríṣìíríṣìí.

Láti rí èyí ṣe, a ó ṣe àyewò ohun tí àwọn onímo ti sọ nípa

àyíká àti ìwòye àwọn àjọ kan tàbí èkejì tí iṣe wọn jẹ mo ètò ìlera

ajẹmo àyíká. A ó wá parí atótónu wa sí ìjíròrò lórí ìlera ajẹmo

àyíká pelú àwòmo àwọn nǹkan tí Olódùmarè dá sí àyíká ọmọ

edá ènìyàn.

Tíorì Àmúlò

Tíorì lítíréso tí a ó máa ṣe àmúlò nínú iṣe yìí ni tíorì lámèéto

ajẹmo àyíká (eco-criticism). Tíorì yìí ni a ó fi ṣe àtegùn láti ṣe

àtúpale àkòrí iṣe wa, ìlera ajẹmo àyíká. Gege bí Ọpefèyítìmí

(1997) ṣe pìtàn re, ìpàdé àpérò ẹgbe àwọn onímo lítíréso níle

Geésì (Western Literature Association) ní ọdún 1970 ni ó bí

Tíorì yìí. Ibi tí won fi ẹnu oro jóná sí níbi ìpàdé náà ni pé kí

àwọn òǹkowé máa gbé iṣe wọn kale lonà tí yóò fi ḿaa ṣe àfihàn

pàtàkì àwọn nǹkan tí Olódùmarè dá sí àwùjọ ènìyàn. Oro ẹnu

Dobie ti Ọpéfèyítìmí (1997) ṣe àgbékale re ṣe é fi ìka to níbí:

They are interesting in examing the relationship of literature and NATURE as a way to renew a reader’s awareness of the non-human world and his/her responsibilities to sustain it. Sharing the fundamental premise that all things are interrelated, they are actively concerned about the impact of human actions on the environment (1997:239). Ohun tí ó mú wọn lokàn ní àyewò ìbáṣepo lítíréso àti àwon edá abemí láti lè je kí àwọn òǹkàwé mọ

Page 4: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

88

Yorùbá: Journal of the Yorùbá Studies Association of Nigeria (Vol. 8 No. 2)

iṣe wọn gege bí olùtojú àwọn nǹkan tí Olódùmarè dá sí àyíká wọn yàto sí ènìyàn. Pẹlú èrò àti ìgbàgbo pé gbogbo nǹkan tí Olódùmarè dá ni ó fi ara kọ ara wọn fún ànfààní kan tàbí èkejì sí ara wọn, ohun tí ó kàn won gbongbon ni ìsesí àwọn ènìyàn lórí àwọn edá tí kì í ṣe ènìyàn ní àyíká.

Èrò Ìsolá (2010) lórí lámeeto ajẹmo àyíká náà ṣe é yewò. Ó gbé

erí kale lórí bí ó ṣe ṣe pàtàkì láti máa tojú àwọn nǹkan tí

Olódùmarè dá sí àyíká wa:

Eco-criticism goes beyond the merely physical; it extends to the emotional and philosophical. When properly nurtured and preserved, the geographical eco-criticism provides food and atmospheric conditions that satisfy the physical and health needs of the people (2010:103-104) Lámeeto ajẹmo àyíká gbòòrò ju ohun tí a lè foju rí ní àyíká nìkan lọ. Ó níí ṣe pelú ìjìnle èrò àti ìmolára edá. Tí a bá tojú àyíká wa bí ó ti to àti bí ó ti yẹ, oúnjẹ yóò sùn wá bo, bee ni àlàáfíà gidi yóò tó wa lowo.

Yàto si àǹfààní kan tàbí èkejì tí èèyàn lè rí gbà nípa títojú àyíká

re, Ìṣolá (2010) ṣe kìlokìlo nípa ṣíṣe àwọn edá àyíká wa bí kò ti

yẹ. Ẹ gbó ohun tí ó wí:

When you cut a single tree in the forest, you destroyed the source of food and abode of some animals, birds and thousands of insects, some of which will perish in their attempt to find new homes. When a species of plants disappears, the human race loses not only animal feed but also

Page 5: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

89

Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyewò Ènìyàn Àti Àwọn Edá Abemí Mìíràn

possible cure for a number of diseases (2010:103-104) Bí a bá gé igi kan nínú igbó, ilé àwọn ẹranko kan, àti ẹgbẹegberún ẹyẹ àti kòkòrò àti onà oúnjẹ wọn ni a ti bàje yẹn. Púpo nínú àwọn ẹranko àti ẹyẹ wonyìí ni yóò kú níbi tí won bá ti ń làkàkà ĺati wá ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí oríṣìí ewé kan bá pare, kìí ṣe pé onà oúnjẹ òòjo àwọn ẹranko kan tán nìkan, ó ṣeé ṣe kí á ti pàdánù ohun tí ó wà fún àwárúnsàn lóríṣìíríṣìí.

Kókó ohun tí Ìsolá (2010) ń sọ níbí ni pé, bí a bá ń soro ìtojú

àyíká, ọmọ ènìyàn ní láti ṣe pelepele pelú àwọn nǹkan tí

Olódùmarè dá sí àyíká wọn. Ohun tí ó tún ṣe pàtàkì sí wa nínú

iṣe yìí ni àkíyèsí Ọpefèyítìmí (1997) pelú bí àwọn èèyàn kan kò

ṣe gba odò/omi láàyè láti sàn bí Olódùmarè ti dá a àti bí oun

pàápàá ṣe ń fe ní agbègbè eko. Oro re nìyí:

Ẹ wo àwọn tó rale kolé sínú irà àti ojú omi lékòó. Tí won ń kó yanrìn dí àwon omi àti irà náà pelú mílíonù àìmọye náírà. Àwọn onímo sáyensi sọ pé’ water finds its own level’, ìyẹn ní pé lojo iwájú, omi tí ẹ rò pé ẹ ti kó yeepe dí lé selerú sínú kò sì fa ilé ríru fún àromọdomọ onílé (o.i48).

Oro nípa bí wíwá epo robì àti èéfín gáàsì ṣe ń ba àyíká je ní

agbègbè Niger Delta ni ó múmú láyà Feghabo (2014). Feghabo

ṣàlàyé pé àwọn ekánsíle epo robì àti èéfín gáàsì to máa ń dì

kùrukùru sí ojú orun ní agbègbè náà ti ba gbogbo àyíká ibe je.

Feghabo fi kún oro re pé ọṣe tí àwọn ekánsíle epo robì àti èéfín

gáàsì yìí ń ṣe lágbègbè náà kò kéré. Bí àpẹẹrẹ, gbogbo àyíká ni

Page 6: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

90

Yorùbá: Journal of the Yorùbá Studies Association of Nigeria (Vol. 8 No. 2)

ó ti di asále, gbogbo àwọn ẹranko ìgbe ni won sì ti sálọ sí ibi tó

jìnnà rere.

Nígbà tí ó ń jábo ìwádìí re, Oyèláràn (2011) ṣàlàyé pe

yàto sí pé àwọn ará ìlú Bámijòkó ní ìpínle Ògùn àti Òkómù ní

ìpínle Edó ní àyíká won gege bí onà láti rí oúnjẹ òòjo, won tún

rí àyíká wọn gege bí orísun ìgbàgbo wọn. Oyèláràn fi kún

atótónu re pé àwọn ará ìlú wonyìí rí àyíká wọn (inú igbó

kìjikìji) bíi ilé ìbọ òrìṣà níbi tí ìmolára tiwọn pelú ti àwọn òrìṣà

wonyìí kò ti ṣeé já tàbí pín. Èyí ni pé inú igbó tí ó wà ní àyíká

yìí ni ó dàbí ilé fún àwọn ìbọ wọn gbogbo. Èyí náà ni ó sì fa

òfin tí won fi léle ni àwọn ìlú wonyí pé ẹnikeni kò gbọdo gé igi

kan, ṣe ọdẹ nínú igbó yìí tàbí dáná sun igbó náà bèlèntàsé ríra

tàbí títà láti fi ko ilé (Oyèláràn o.i 15).

Ìwádìí Oyèláràn, (2011) fere ṣe déédéé pelú ti Bunza,

(2007). Bunza sàlàyé pé ní agbègbè Zúrú ní gúúsù ìla òòrùn

oríle-èdè Nigeria, ojúbọ kan wà níbe tí wọn ń pè ní Grimace.

Bunza fi kún àlàyé re pé ẹnikeni kò gbọdo ṣe ọdẹ ní agbègbè

náà. Nítorí pé ẹnikeni tó bá pa ooni tó je òrìṣà tí wọn ń bọ, tó sì

dúró bíi Ọlorun agbègbè náà yóò kú pelú ooni náà ni.

A lérò pé irú ètò báyìí ni Santangelo (2007) ri tí ó fi sọ pé

‘that the eco-critics insist that in literary studies, non-human

nature must be treated as having an existence and value’. Èyí ni

pé kí lámeeto lítíréso ajẹmo àyíká tàbí oníṣe onà ajẹmo àyíká

máa fi iṣe rẹ ṣe àfihàn pàtàkì àwọn edá àyíká ti won kì í ṣe

ènìyàn wonyìí pelú bí ó ṣe je pé wọn ni ìwà, emí àti ànfààní tàbí

ìwúlò kan.

Slaymaker (2007) pè fún ṣíṣe déédé láàrin ènìyàn àti

àwọn edá ti won kì í ṣe ènìyàn ní àyíká. Oro re lọ báyìí:

Page 7: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

91

Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyewò Ènìyàn Àti Àwọn Edá Abemí Mìíràn

Environmental justice as a global paradigm will be used in the world market place when decisions are made about production consumption of resources and pollution caused by modernization, industriliazation and population growth. Dédé àjẹmo àyíká àti àwọn ènìyàn ibe gege bí ọpá òdiwon gbogbogboo ni a ó máa ló ni ọjà àgbáyé nígbà ti ìjíròrò tàbí ìfoŕikoŕi bá ń wáyé nípa ìpèsè àwọn nǹkan kan, lílò àwọn nǹkan tí Olódùmarè fi ta àwùjọ lóre àti àwọn nǹkan tí ó ń bá àlàáfìà ìlú je, ti igbe ayé otun, ìdókòwò, àti bí èèyàn ṣe po tó dá síle.

Oro Oyèláràn (2011) ni a ó fi ka atótónu àwọn onímo àjẹmo

àyíká níle. Oyèláràn tan ìmole sí ibi tí ó jọ pè òkùnkùn fe wá

nínú oro Slaymaker òkè yìí. Ohun tí Oyèláràn sọ ni pé

we do not believe in an undesirable sophiscated modernization and inducstrilization, as they do more harm than good… That many highly significant environmental changes were and are being achieved by non-industrial societies like Nigeria. Àwa kò ní ìgbàgbo nínú ìgbé ayé otun yeye àti ìdókowò ìrégbè nítorí pé ọṣe tí won ń ṣe jù dáadáa wọn lọ. Pé àìmọye àyípadà tó ni ìtumo ni ó ti ń dé bá agbègbè tàbí àyíká ti wọn kò dágbálé ètò olókoowò ńláńlá bíi ti orílẹ-èdè Nàìjìríà tí ó sì tún ń dé bá wọn lowolowo.

Page 8: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

92

Yorùbá: Journal of the Yorùbá Studies Association of Nigeria (Vol. 8 No. 2)

Ohun tí gbogbo àwọn agbátẹrù tàbí lámèèto tíorì àjẹmo àyiká ń

tẹnumo ni pé bí Olódùmarè ṣe dá edá ènìyàn pelú iṣe tàbí ìwúlò

kan tàbí òmíràn láyé láti ṣe fún Olódùmarè, náà ni Olódùnmarè

dá àwọn edá mìíràn ti wọn kì í ṣe ènìyàn fún ànfààní kan tàbí

èkejì. Kókó atótónu àwọn onímo lámeeto àjẹmo àyíká ni pé kí

àwa ènìyàn àwùjọ rí àwọn edá àyíká wà gege bí ohun tó ní ìwà,

emí, ìmolára, àti ànfààní kan tàbí òmíràn. Láti tọpinpin irú

ànfàní tí a menu bà yìí, èrò àwọn onímo ni pé gígé igi lule láìní

ìdí kan pàkàkì kò dára. Sísán tàbí gígé àwọn ewéko àyíká dànù

kò sunwon. Bee náà ni pípa àwọn ẹranko ilé àti ti ìgbe ni

ìpakúpa kò tonà. Dídí onà mo odò/omi láti sàn kù díe káàtó.

Dídána sun igbó orò tàbí ojúbọ òrìṣà kò bójúmu. Pé bí a bá ń gé

igi nígbó, kí a máa fi oro ro ara wa wò.

Ìgbàgbo Yorùbá nínú Olódùmarè nípa àwọn Edá Àyíká

Yorùbá gbàgbo pé kì í ṣe edá ènìyàn nìkan ni ó ní ìwà, emí,

ìmolára àti ànfààní kan tàbí èkejì. Bí ènìyàn ọmọ adáríhunrun ṣe

ní ẹmí àti ìmolára nǹkan bee ni àwọn edá tí wọn kì í ṣe ènìyàn

bí i igi/ewéko, ẹranko (tilé àti tìgbe), ẹja inú omi, òkè/àpáta àti

odò/omi àti ẹyẹ ojú orun náà ni. Yorùbá tún gbàgbo pé àwọn

ohun ẹlemìí kan tí wọn kì í ṣe ènìyàn sí wa tí ó je pé a jọ ń gbé

ní àyíká ni. Àwọn ohun ẹlemìí wonyìí le je obọ, iwin àti

àlùjonnnú oríṣìíríṣìí. Lóòóto ni pé a kò rí wọn, ṣùgbon Yorùbá

gbàgbo pé wọn ń bẹ àti pé wọn ní emí àti irúfe agbára kan,

(Abimbola, 1975, 1976; Ìsolá, 1992, 2010).

Yorùbá gbàgbo pé oríṣìíríṣìí ẹranko ìgbe ló wà àti pé

àwọn ẹranko mìíràn ní agbára láti yí padà di ohun tí wọn bá fe.

Page 9: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

93

Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyewò Ènìyàn Àti Àwọn Edá Abemí Mìíràn

Àgbonrín àti ẹfon a máa yíra padà di ìnájá, òǹtajà tàbí òǹràjà

nínú ọjà ọmọ ènìyàn, (Olayemi, 1975; Obed, 2001; Ìsolá, 2010).

Yorùbá tún gbàgbo pé àwọn iginìyán wà. Èyí ni pé àwọn igi kan

wà ti wọn ní agbára àìrí kan. Pé àwọn emí alágbára kan wà nínú

igi ti Yorùbá ń pè ní oro, (Bamgbose, 1974; Ìsolá, 1992). Yorùbá

gbà pé kì í ṣe ara ènìyàn nìkan loore wà, ‘igi tó bá ṣeni lóore làá

wárí fún’, (Ajíbádé àti Rájí, 2011). Lára ìgbàgbo Yorùbá tún ni

pé emí àìrí le wà nínú afefe, òkè tàbí apáta. Gbogbo odò ni ó ni

alákòóso wọn àti pé àwọn edá inú odò náà ni àwọn agbára àìrí

kan bee náà ni wọn ní ìmolára nǹkan.

Esìn Yorùbá

Gege bí a ṣe feeke lù ú ní ìbere, esìn Yorùbá rọ kiri ká ìgbàgbo

wọn nínú Olódùmarè pelú oríṣìíríṣìí orúkọ ti wọn fún un láti ṣe

àpèjúwe re. Gbogbo àwọn nǹkan tí ó tóbi, tí ó lágbára, tí ó ba

ni lerù tàbí tí ìwà wọn tojúsúni tàbi koni lóminú ni Yorùbá gbà

pé ó yẹ kí àwọn wáárí fun. Ìdí nìyí tí wọn fi máa ń kóbì bọ òkè,

odò, igi ńláńlá, abbl. Bíbọ ti Yorùbá ń bọ àwọn nǹkan tí a

dárúkọ wonyìí kò ṣeyìn ìgbàgbo wọn pé agbára àwọn nǹkan

wonyí po débi pé won lè fi aburú kan tàbí èkejì kan ènìyàn. Pé

bí a bá lè máa rọ àwọn emí àìrí wonyí, láti ara bíbọ won nípa

fífún wọn ni ohun tí a mo pé wọn feràn láti máa je, won kò ni le

fi aburú kankan kan ènìyàn. Lára emí àìrí ti Yorùbá gbàgbo pé

won ní ìkápá lórí edá ènìyàn ní òkú orun. Ìpèdè Yorùbá kan ní

“ìgbìn làá lù fún òósálá kó tó máa jó, ẹkún làá sun fún òkú orun

kí wọn ó tó máa gbéni”. Fífún òkú orun ní ohun tí wọn ń fe ni ó

fara jọ ekùn tí a sọ lókè yìí. Onà kan pàtàkì ti Yorùbá fi ń

sàponlé òkú orun ni nípa gbígbé egúngún, òkú pípè, àti sísun

Page 10: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

94

Yorùbá: Journal of the Yorùbá Studies Association of Nigeria (Vol. 8 No. 2)

ìrèmojé, (Babayẹmí, 1980; Àjùwon, 1982; Àmoó, 1982;

Fátókun, 2005). Lára ohun tí ó tún ṣe àfihàn esìn níle Yorùbá ni

bíbọ òrìṣà. Oríṣìírìṣìí ni òrìṣà ti Yorùbá máa ń bọ (Olúpònnà,

2011; Ìdòwú, 1996). Lára àwọn irú òrìṣà bee ni òrìṣà tí wọn fi tẹ

ìlú kan dó tàbí àwọn àkọni tí wọn bínú wọle tàbí tí wọn di igi

tàbí òkè tàbí àpáta. Díẹ lára òrìṣà tàbí ìbọ níle Yorùbá ni Òòṣálá,

Ògún, Ṣàngó, Ọya, Oṣun, Òrìṣà oko, Èṣù abbl, (Dáramolá àti

Jeje 1967).

Lára ohun tí Yorùbá máa ń bowo fún tí ó tún lapa nínú

esìn wọn ní pepefúrú ti wọn máa ń ṣe fún àwọn àje àti oṣó tí

wọn gbàgbo pé àwọn ni Olódùmarè kó òkun ayé lé lowo,

(Ilésanmí, 2014). Bí ó tile je pé ènìyan lásán kò lè mo won,

agbára wọn po àti wí pé ó fere ma sí àrà ti wọn kò lè fi ènìyan

dá. Gbogbo onà ti Yorùbá gbé ìsìn/esìn wọn ká ló níí ṣe pelú

àkíyèsí àti ìbowo fún àyíká wọn. Gbogbo ohun ti Olódùmaré dà

sí àyíká tí Yorùbá ti bá ara re ni ó ń ṣe wọn ní kàyèéfì, tí ó ń

derù ba won. Èrò àti ìgbàgbo Yorùbá ni pé àwọn edá tí wọn kì í

ṣe ènìyàn wonyí ṣùgbon ti agbára wọn po yẹ ní bíbo kí àlàáfìà ó

le jọba ní àyíká àti àwùjọ lápapo.

Èrò báyéṣerí Yorùbá nípa Àyíká

Leyìn ìwádìí ìjìnle àti opolọpo àkíyèsí, Yorùbá wòye pé kì í ṣe

pé gbogbo nǹkan tí Olódùmarè dá dára nìkan ko, àwọn náà ni

ìwà, emí àti ìmolára nǹkan bíi ti ènìyàn, ọmọ adáríhunrun. Won

ní agbára àìrí kan, wọn sì kún fún opolọpo àǹfààní fún olùgbé

àyíká tí wo n bá wà.

Page 11: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

95

Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyewò Ènìyàn Àti Àwọn Edá Abemí Mìíràn

Ìlera Ajẹmo Àyíká: Àyewò ìbáṣepo láàrin ènìyàn àti àwọn

e dá abemí mìíràn

Lóòóto ni pé àwọn onímo kan gbé ìwádìí wọn jáde pé fífe ti aye

ń fẹjú lójoójúmo àti pípo ti ènìyàn ń po síi lórí ile ló ń pagidínà

àlàáfíà àwọn edá abemí tí won yàto sí ènìyàn, ṣùgbon le nu

looloo yìí àwọn onímo mìíràn ti gbé oriṣìíriṣí erí jáde pé kì í ṣe

pípo tí ènìyàn po ló ń pagidínà àlàáfíà àwùjọ bi ko ṣe ètò ìṣèlú

tó ro mo ìdókòwò alàdàáńlá (Fearnside, 1993; Hultric et al,

2002; Armitage, 2002; Glaser et al, 2003; Hultric, 2005). Díe

lára irú ìdókòwò tí won sọ pé ó ń pagidínà àlàáfíà àwọn edá

abemí wonyí ni kíkó ẹja lódò lopo yanturu fún títà; àti pípale

rẹpẹtẹ fún agbo mààlúù; láti máa sìn fún títà.

Ìwé ìròyìn Daily Trust ọjo Móńdè, 31-08-2015 gbé

ìròyìn kan jáde tó dálé orí ìlera ajẹmo àyíká. Ìwé ìròyìn náà ní

ìwádìí ìjìnle ti fi ìdí re múle pé àìmọye kòkòrò kéékèèké tí wọn

kò ṣeé fi ojú rí, ni won máa ń ba eruku kowoo rìn. Kókó ohun tí

ìròyìn náà tẹnumo ni pé àwọn kòkòrò tí won máa ń ba eruku

kowoo rín wonyìí máa ń ṣe àkóbá fún ìlera ènìyàn ni.

Opolọpo ariwo gèè tí ó ń ti àwọn ilé ìjosìn, ilé ìtura àti ilé

ìgbafe wà àti bí won ṣe ń pagidínà àlàáfìà ará ìlú ni oro olóòtú

ìwé ìròyìn Daily Trust ọjo Ẹtì, 28-08-2015 dálé lórí. Ìwé ìròyìn

náà ṣàlàyé pé o ti di bárakú fún àwọn onílé ìtura àti àwọn tó ń ta

oúnjẹ àti ọtí láti máa yín rekoodù orin wọn sókè lalaala láìnáání

ọse tí irú ìhùwàsí bee ń se ní àyíká. Ìwé ìròyìn náà tún fi kún

àlàyé re pé ariwo tí àwọn olùjosìn mùsùlùmí àti àwọn ọmọleyìn

Jésù máa ń pa ní òru níbi ìwàásù àti ìso òru ń kóbá àlàáfìà

lápapo.

Page 12: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

96

Yorùbá: Journal of the Yorùbá Studies Association of Nigeria (Vol. 8 No. 2)

Kókó ohun tí ìwé ìròyìn yìí ń wí ni pé bí a bá ń wá àlàáfìà ní

àyíká, ìwon ni nǹkan dùn mọ nípa àpojù ariwo ní àyíká.

Lórí oro ìlera àjẹmo àyíká ewe, àgbékale ètò ìṣàtúnṣe

ìjọba àpapo, Ọlogbondàà-arónilágbára Àjẹmo Ọroajé àti

Ìdàgbàsókè (NEEDS, 2005) pè fún àkíyèsí. Kò sí kí oro àyíká

má kàn NEEDS tele, níwon ìgbà tó je pé àfojúsùn re ni

ọgbondáá oro ajé àti ìdàgbàsókè àwùjọ tàbí àyíká. Kókó iṣe

merin otooto ni àfojúsùn NEEDS, (2005). Iṣe merin tó fe máa ṣe

ní eka ìlera àwùjọ ni ṣíṣe àwárí onà ti àwọn nǹkan egbin àti ìdotí

ṣe ń wáyé ní àyíká àti bí a ṣe lè kó wọn kúrò níle. Nǹkan kejì ni

èyí tí ó níi ṣe pelú ìlàkàkà lórí bi gbogbo àyíká wa kò ṣe ni di

aṣále. NEEDS, (2005) ṣàlàyé pe ṣaájú àsìkò yìí, àyíká wa ní

Nìàjíríà kún fún àwọn igbó kìjikìji ṣùgbon lenu looloọ yìí aṣále

ti fe gbórí lowo igbó kìjikìji. Ohun kẹta tí ó tún fe fara pe èkejì

ni NEEDS pè ní ṣíṣe àwon ẹranko kan lojo sí àwọn ààyè kan, tó

dára, tó tejú, tí yóò si ṣe déédéé pelú ibi tí àwọn ẹranko náà yóò

ní ìfe sí. Èrò NEEDS lórí èyí ní pé, bí a bá tojú àwọn ẹranko

ìgbe tí wọn ṣe pàtàkì wonyìí, tí a ṣe won lojo sí ibi tí àwọn

ènìyàn ti le máa wá wò won yóò ṣe ànfààní fún àyíkà àti oríle-

èdè lápapo. Ètò kẹrin tí NEEDS gbé kale ni ó pè ní gbígbógun ti

àwọn nǹkan tí ó lè ba àlàáfìà àyíká je. NEEDS ni ó yẹ kí òfin

oríle èdè wa lágbára láti lè fòpin sí oro àwọn nǹkan tí ó ń

pagidínà àlàáfìà ìlú. NEEDS, (2005) fi kún àlàyé re pé lára

nǹkan tí ó ń dín àlàáfìà ìlú kù ni ekànsíle epo robì àti èéfín gáàsì

tí ó máa ń di kùrukùru sí ojú orun bíi síṣú òjò.

Bí a bá wo kókó nǹkan merin tí NEEDS gbé kale yìí, a ó kíyèsí

pé gbogbo re náà ló jẹ mo ìlera àti àlàáfìà àyíká, ọmọ edá ènìyàn

àti àwọn edá tí won kì í ṣe ènìyàn. Màjàdùnmí, màjàdunra-ẹni ni

Page 13: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

97

Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyewò Ènìyàn Àti Àwọn Edá Abemí Mìíràn

oro títojú àyíká je nítorí pé bí ìgbà tí ènìyàn ń tojú ara re náà ni.

Ní bàyìí, ẹ je kí á wo àwọn onà ti àwọn edá àyíká lè gbà wúlò

fún ìlera ọmọ edá ènìyàn lápapo.

Ìwúlò afefe fún ìlera edá ènìyàn

Mímí sínú àti sóde ni ó ya àlààyè ènìyàn soto kúrò láàrin àwọn

òkú. Bí ènìyàn kò ba ti lè mí mo, ó ti kú nìyẹn. Ohun ti

Wilkinson (2011) sọ nipa ìbáṣepo ènìyàn àti àwon edá abemí

mìíràn ni pe

The flora of the earth produces the oxygen that is breathed by the fauna and in turn the fauna exhale the carbon-dioxide that the flora need to live and that humans cannot live without either. Afefe tàbí èémí ti àwọn igi oko àti ewéko ìgbe ń mí síta tí a pè ni èémí àmísínú ni àwọn ẹranko ìgbe n mi sínú fún ìsemí àti àlàáfíà wọn, nígbà ti ó si tún je pé èémí tàbí afefe tí ó ń jade lára àwọn ẹranko ìgbe wonyìí ti a pe ni èémí àmísóde naa ni àwọn igi àti ewéko ìgbe nílò fún ìsemí àti àlàáfíà ti wọn, àti pe irúfe afefe tàbí èémí oríṣìí méjèèjì wonyìí ni ó wúlò fún ìsemí ọmọ edá ènìyàn.

Wilkinson (2011) wa fi èrò rẹ gúnle pé:

In fact human beings cannot breath unless both flora and fauna survive and thrive on the earth. The very air we breathe, and the food we eat, the medicine that cures us, and the water that keeps us alive would not exist were it not for flora and fauna. All things in an ecosystem are interdependent. The existence of one specie may depend on the health of another.

Page 14: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

98

Yorùbá: Journal of the Yorùbá Studies Association of Nigeria (Vol. 8 No. 2)

Lódodo, ènìyàn ko le ni ìsemí àlàáfíà bí kò ṣe pé àwọn edá abemí yòókù yàto sí ènìyàn bá wà dáadaa; èyi ni wíwà ní bí ó ṣe to àti bó ṣe yẹ lórí ile ayé. Afefe ti a ń mí sínú àti sóde, oúnjẹ ti a ń jẹ, egbòogi ti ó ń wò wá sàn, àti omi ti a ń mu ìbá má wáyé bí kò ṣe nípase àwọn nǹkan abemí wonyí. Gbogbo nǹkan ti Olódùmarè da ni wọn jọ gbára le ara wọn fún àǹfààní kan tàbí òmíràn. Ìsemí nnkan abemí kan le gbára le ìwà tàbí alaafia nǹkan abemí mìíràn.

Onà mìíràn pàtàkì tí a fi lè mú ìlò afefe ni òkúnkúndùn nípa

ìlera wa ni gbígbé ní àyíká tó gbààyè. Bí àpẹẹrẹ tí a bá ko ilé, ki

a fi ojú fèrèsè tí ó fe, ti afefe yóò fi máa rí ààyè dé odo wa bí a

bá wà nínú ilé wa. Lára ohun tí ó tún ṣe pàtàkì nínú oro afefe ni

ètò gbíngbin igi àti àwọn òdòdó aláràbarà sí àyíká wa. Àwọn igi

àti òdòdó olóòórùn dídùn wonyìí máa ń pèsè afefe àlàáfíà tí ó

wúlò fún ìgbáyégbádùn ọmọ ènìyàn àti àyíká lápapo.

Ìwúlò Odò/Omi ní Àyíká

Yàto si pé odò je ilé ẹja àti àwọn edá inú omi yòókù ti won

wúlò fún ènìyàn gege bí oúnjẹ, odò náà ni a ti máa ń rí omi ti a

ń lò ni oríṣìíríṣìí onà. Oro Yorùbá kan lọ báyìí pé ‘a kì í bómii

sotá, omi la bùwe, omi la bù mu’. A kò tún le sese máa sọ rírí

omi láwùjọ. Gege bí a ṣe sọ nínú ìfáárà wa, Yorùbá gbàgbo pé

àwọn odò ńlánlá ni emí àti irúfe agbára kan. Pé bi ènìyàn bá mo

ètò àti onà rẹ, àwọn odò wonyí lè ran edá lowo fún ìlera wọn.

Ìdí nìyí tí àwọn Yorùbá fi máa ń bọ odò ńláńlá àdúgbò wọn.

Won tún máa ń sọ ọmọ wọn ní orúkọ tó jẹ mo omi tàbí odò kan;

Page 15: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

99

Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyewò Ènìyàn Àti Àwọn Edá Abemí Mìíràn

Omítóògùn, Omilabú, abbl. Àpẹẹrẹ irú odò báyìí ni ti Oṣun

Òṣogbo tí wọn máa ń bọ lodọodún.

Ìwúlò Igbó Kìjikìji ní Àyíká

Bí a bá ń soro igbó kìjikìji tó je ara àwòmo àyíká Yorùbá, kò sí

àníàní pé igbó kìjikìji je ilé awọn igi ńláńlá àti àwọn ẹranko

ìgbe. Èyí nìkan ko, inú igbó kìjikìji ni a tún lè pè ní ilé àwọn

òrìṣà, pàápàá ìgbàle egúngún. Yàto sí pé àwọn igi ńláńlá kan bi

igi ìrókò, ogànwó, arère, omo, igi opẹ, abbl máa ń lale hù pelú

àṣẹ Olódùmarè, tí won sì wúlò fún ilé kíko àti oríṣìíríṣìí àǹfààní

mìíràn fún ọmọnìyàn, a tún le gbin igi owó bíi kòkó, robà, o pẹ,

ọsàn, abbl. Inú igbó tún je orísun onà oúnjẹ fún edá ènìyàn.

Àwọn ọdẹ a máa pa ẹran tı ó wúlò fún títà tàbí jíje. A le sán

igbó láti gbin àwọn ohun tenu ń jẹ kan sí àyíká wa.

Ìwúlò Òkè ní Àyíká

Òkè ńláńlá máa ń pèsè ààbò gege bí ibi ìsádi kúrò lowo otá

pàápàá lásìkò ogun tàbí ote kan. Yàto sí èyí, ohun tí a gbo ni pé

àwọn nǹkan àlùmoonì máa ń wà nínú àwọn òkè àti àpáta ńláńlá.

Ewe, Yorùbá tún gbàgbo pé àwọn emí alágbára kan máa ń fi inú

àpáta tàbí òkè ńláńlá ṣe ilé àti pé ènìyàn le wá ìrànlowo kan tàbí

òmíràn lọ sórí òkè kan. Bí a bá ní kí a fẹ oro òkè lójú, a ó kíyèsí

pé opolọpo àwọn ènìyàn ni won feràn làti máa lọ sí orí òké kan

tàbí òmíràn láti lọ gba àdúrà tàbí wá agbára kan. Igbàgbo irú

àwọn ènìyàn báyìí kò ṣe lórí pé irúfe agbára àìrí tàbí ìmísí

Olódùmarè máa ń gbé inú òkè ńláńlá. Ju gbogbo re lọ, afefe

àlàáfìà máa ń ti orí òkè ńláńlá wà, èyí tí ó wúlò fún ìlera ọmọ

edá ènìyàn.

Page 16: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

100

Yorùbá: Journal of the Yorùbá Studies Association of Nigeria (Vol. 8 No. 2)

Ìlera ènìyàn àjẹmo Àyíká tí o ro mo tewétegbò

Adéoyè, (2005) ń ṣe àfihàn ìgbàgbo Yorùbá nípa oògùn ìbíle

Yorùbá nígbà tí o sọ pé ‘Ọlorun kò kọ aájò’. Adéoyè tesíwájú

láti sọ pé kíko ni a máa ń kó oògùn àti pé ẹni ti yóò bá ko oògùn

gbọdo je ẹni ti ó ní sùúrù àti ìfaradà nítorí pé ‘opolọpo ọdún ni

ekose ìṣègùn máa ń gbà kí onítohún tó le gbówo’. Ó wá pìtàn pé

ọkùnrin kan ńbẹ nígbà kan tí orúkọ re ń je Àágberí. Ó ní

ọkùnrin yìí rí ìdí egbòogi àti pé lodo re ni opolọpo adáhunṣe ti

kose ìṣègùn. Kókó inú oro Adéoyè ni pé, ọjo ti pe tí ìran Yorùbá

ti kọbíara sí ìlò tewétegbò fún ìlera wọn pelú erí pé wọn máa ń

ko ọ gege bí iṣe àṣelà ni.

Fádípe (1970) pín oògùn níle Yorùbá si, (1) awàrùnsàn,

mojèlé, àpèta/àfikàn, ajẹméèwo, èpè, oṣó àti àje àti oògùn

ajẹmesìn. Fádípe ṣàlàyé pé bí oògùn ṣe lè jẹ mo agbára emí àìrí

tàbí ohun ìkoko, bee nàá ni a rí oògùn tó jẹ mo àkójọpo egbòogi

tó fe lo ní ìlànà ìmo sáyensì. Èyí ni oògùn tí a lè fojú rí kí a sì ṣe

àkíyèsí oná tí ó ń gbà siṣe.

Oro ẹnu akowé ìlera Eko ìgbà kan tí Fádípe gbà síle ní

ọdún (1931) túṣu déle ìkòkò nípa oògùn awàrùnsàn níle Yorùbá.

Ge ge bí ó ti wí:

Medicine is among most tribes associated with magic or juju. But among the Yoruba the separation is almost complete, and there exists a society of native doctors. Anyone may practice medicine among the Yoruba and to a certain extent everyman is his own physician…. The principal remedies are for purgative and fever and some at least efficacious. Many preparations are known for the treatment of gonorrhea.

Page 17: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

101

Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyewò Ènìyàn Àti Àwọn Edá Abemí Mìíràn

Ìlò egbòogi ń bẹ láàárín àwọn eyà tó jẹ mo oògùn tó ńíi ṣe pelú emí àìrí tàbí májíìkì. Ṣùgbon ní ti ìran Yorùbá, ìlò tewétegbò fún ìlera ènìyàn hànde yàto sí oògùn àjẹmo emí àìrí tàbí májíìkì nìkan bí ó ṣe je pé àwọn awàrùnsàn ìbíle wà. Gbogbo ènìyàn ni ó fere je dókítà ara re níwon ìgbà tó je pé oníkálúkù ló máa ń wá onà láti tojú ara re nípa ìlò tewétegbò. Pàtàkì nínú àwọn àìsàn tí wọn ń fi tewétegbò kojú ni ìgbẹ àti ibà. Won tún ní oríṣíìríṣìí àpapo tewétegbò fún àìsàn àtosí.

Ohun tí Johnson (2009:144) sọ nípa oògùn ìbíle Yorùbá ni pé

àwọn ènìyàn kan wà tí a le pè ní dókítà gege bí iṣe wọn. Àti pé

àwọn wonyìí ni ẹni àsárépè bi nǹkan/àìsàn òjiìjì bá yọjú. Orúkọ

wọn ni adáhunṣe. Johnson fi kún àlàyé re pé bí ó tile je pé kò sí

ilé ìwòsàn kan pàtó, síbe, àwọn adáhunṣe wonyí ti ṣe àwárí

àwọn tewétegbò kan tí wọn fi ń kojú/kápá àwọn àìsàn bíi ete,

àrùn ọpọlọ, ọgbe inú, abbl. Iṣe tí a fúra pé atótónu òkè yìí ń rán

sí àwùjọ ni pé Olódùmarè tó dá edá ti mo pé àìsàn kan tàbí

ìpèníjà kan lórí ìlera wọn yóó máa wà. Ìdí nìyí tí ó fi dá

oríṣìíríṣìí ewé, egbò àti nǹkan mìíràn sí àyíká ọmọ ènìyàn láti le

wúlò fún ìwòsàn àrùn kan tàbí òmíràn. Ohun tí a rí fàyọ nínú iṣe

àwọn onímo nípa oògùn ìbíle Yorùbá meteeta tí a yewò nínú

pépà yìí ni pé onà méjì pàtàkì ni a le pín oògùn ìbíle Yorùbá sí.

Onà kìn-ín-ní ni oògùn ajẹmo tewétegbò, èyí tí ó je pé gbogbo

ènìyàn ni a fere le pè ni dókítà nígbà tí èkejì je mo oògùn tó níi

ṣe pelú ìmísí Olódùmarè tàbí ìgbàgbo nípa àwọn edà tí Ó dá sí

àyíká ọmọ ènìyàn fún ìlera àti àlàáfìà wọn.

Page 18: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

102

Yorùbá: Journal of the Yorùbá Studies Association of Nigeria (Vol. 8 No. 2)

Àgbálọgbábo

Kókó ohun tí a jíròrò lé lórí nínú pépà yìí ni àjọsepo tó yẹ kó wà

láàrin edá ènìyàn àti àwọn edá yòókù ti Olódùmarè jọ dá wọn

po ní àyíkà. Pépà yìí menu ba oríṣìíríìṣìí àwọn nǹkan tí wọn wà

ní àyíká ọmọ ènìyàn bíi igi, odò, òkè /àpáta, abbl gege bí wọn ṣe

wúlò fún ìlera ọmọ ènìyàn. A ṣe àyewò ohun tí àwọn onímo ti

wí nípa àyíká àti bí a ṣe lè tojú àyíká ọmọnìyàn láti lè fún wa ní

ìlera tó péye. Onà ibi tí tewétegbò ti wúlò fún ìlera ọmọ ènìyàn

ni a parí àníyàn pépà yìí sí.

Ó hàn nínú iṣe ìwádìí yìí pé púpo nínú àwọn nǹkan tí

Olódùmarè dá sí àyíká edá bíi odò (omi), igbó kìjikìji, ewéko,

òkè ńláńlá, apáta, ẹranko ìgbe àti tile ló wúlò fún edá ènìyàn.

Bákan náà ni a toka sí àwọn ohun tí ó ń pagidínà àlàáfíà àwọn

edá abemí bíi kíkó ẹja lódò lopo yanturu fún títà, pípale rẹpẹtẹ

fún agbo màlúù láti máa sìn fún títà àti opolọpo ariwo gèè. Pépà

yìí wá fi gbèdéke lé e pé níwon ìgbà tó je gbogbo mùtúmùwà ló

mo pé àlàáfìà, ìlera tó péye ni ó ṣe kókó jù lọ nínú ìse mí ayé

ènìyàn, ó yẹ kí tolórí tẹlemù gbìyànjú àti máa tojú àyíká wọn ní

gbogbo ìgbà. Kí won máa gbé ní àyíkà tó mo tónítóní. Bákan

náà kí won má ṣe gé igi lule láìní ìdí. Bee ni dídí onà mọ

odò/omi pelú kíko ilè sí ojú odò kù díe káàtó.

Ìwé Ìtokasí

Abimbọla, W. (1976) Ifa: An Exposition of Ifa Literary Corpus. Ibadan: Oxford University Press.

Adebọwale, B. (2012) Reincaination in Plato and Yoruba Traditional Belief Ninu Yorùbá: Journal of Yoruba

Page 19: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

103

Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyewò Ènìyàn Àti Àwọn Edá Abemí Mìíràn

Studies Association of Nigeria. Vol. 7. No.1. Ibadan: Hakolad Prints.

Adeoye, C. (2005). Àsà àti Ìṣe Yorùbá, Ìbàdàn: University Press.

Ajibade, G. ati Raji, S. (2011) Ìsowolo-èdè Àlàbí Ògúndépò, Apá kìníní. Akure: Masterprint Publishers.

Ajuwọn, B. (1981). Ìrèmòjé Eré Ìsípá Ọde. Ìbàdàn: University Press Ltd.

Amoo, A. (1989). Àròfò Òkú Pípè. Ìbàdàn: Longman Plc.

Armitage, D. (2002). Social Institution Dynamics and Political Ecology of Mangrove Forest Conservation in Central Sulawesi; Indonesia: Global Environmental change.

Ayantayọ, J. (2009). Fundamental of Religious Ethics. Ibadan: End-time Publishing House.

Babayemi, S. O. (1980). Egúngún Among the Oyo Yorùbá. Ibadan: Board Publication Ltd.

Bamgbose, A. (2007). The Novels of D.O Fagunwa: A Commentary. Ibadan: Nelson Publishers Ltd.

Daily Trust Editorial (2015). Controlling Noise Pollution. Abuja: Daily Trust Ltd.

Daily Trust Editorial (2015). Household Dust Harbours Thousands of Microbial Species. Abuja: Daily Trust Ltd.

National Planning Commission of Nigeria (2005) National Economic Empowerment and Developmental Strategies (NEEDS). Abuja: b3 Communication Ltd.

Bunza, M.U (2007) Girmace Shrine Among the Dakarkari in Zuruland: An Examination of AfricanTraditional Religion

Page 20: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

104

Yorùbá: Journal of the Yorùbá Studies Association of Nigeria (Vol. 8 No. 2)

in North-Western Nigeria KADA; Journal of Liberal Arts, Vol. 1.No 1. Kaduna State University, Kaduna.

Fadipe, N. A. (1970). The Sociology of the Yoruba. Ibadan: University Press.

Fagunwa, D. O. (1938). Ogboju Ode Ninu Igbo Irunmole. Ibadan: Nelson publishers Ltd.

Fatokun, S. A. (2005). Afican Traditional Religion and Belief Systems ninu Ajayi, S.A. (ed) African Culture and Civilization. Ibadan: Atlantis Books.

Feghabo, C. (2014). Alienation and Ecoactivicism in Selected Works on the Niger-Delta. Unpublished Ph.D Thesis, English Department, University of Ibadan.

Fearnside, P.M. (1993). Deforestation in Brazillian Amazonia: The effect of population and land Tenure. AMB10: A Journal of the Human Environment, 22, 8, 537-545.

Glaser, M. (2006). The Social Dimension in Eco-system Management: Strengthens and Weaknesses of Human Nature Mind Map. Centre for Human Marine Econology (ZMT). Germany: University of Breven Press.

Hultric, M.; C. Folke and N. Kantsky (2002). Development and Government Policies of the Shrimp Farming Industry in Thailand in Relation to Mangrove Ecossytems. Ecological Economics, 40, 3441-455.

Hultric, M. (2005). Lobster and Couch Fisheries of Belize: A Historical Sequencial Exploitation. Ecology and Society 10,1,21.

Idowu, B. (1996) Olodumare: God in Yoruba Belief. Ikeja: Longman Nigeria, PLC.

Page 21: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

105

Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyewò Ènìyàn Àti Àwọn Edá Abemí Mìíràn

Ilesanmi, M. (2014). Obìnrin: A Cultural Assessment of Yoruba Women. Ile-ife: Astra Multimedia.

Isola, A. (2010). Making Culture Memorable: Essays on Language, Culture and Development. Ibadan: DB. Martoy Books, and Hope Publications Ltd.

Isola, A. (1990). Ogún Ọmọdè. Ibadan: University Press.

Johnson, S. (2009). The History of the Yoruba: Lagos: CSS Books Ltd.

Obed, A. (2001). Antelop (Woman) and Buffalo (Woman): Contemporary Literary Transformation of a Topos in Yoruba Culture. A Thesis submitted to the School of Oriental and African Studies, University of London.

Olayemi, V. (1975). The Supernatural in the Yoruba Folktales ninu Abimbola, W. (ed) Yoruba Oral Tradition: Poetry, Music, Dance and Drama. Ibadan: Ibadan University Press.

Oluponna, J.K. (2011). City of 201 Gods: Ile-ife in Time, Space and Imagination. London: University of California Press.

Opefeyitimi, A. (1997). Tíorì àti Ìsọwolo-Èdè. Ilé-ife: Obafemi Awolowo University Press.

Oyelaran, (2011). Written in Flames: A Tale of an Environment in Peril: An Inaugural Lecture delivered at the Univeristy of Ibadan.

Santangelo, B. (2007). Different Shades of Green: Ecocriticism and African Literature ninu Olaniyan, T.and Quayson, A. (ed) African Literature, An Anthology of Criticism and Theory. UK: Blackwell Publishing.

Page 22: Ètò Ìlera Ajẹmáyìíká: Àyèwò Ènìyàn Àti Àwọn Ẹ ̀dá ̣ Abèmí ...ysan.org/mgt/uploaded/165_Eto ilera ajemayika.pdf · ilé tuntun mìíràn àti oúnjẹ. Tí

106

Yorùbá: Journal of the Yorùbá Studies Association of Nigeria (Vol. 8 No. 2)

Slaymaker, W. (2007). Echoing the Other(s): The Call of Global Green and Black African Responses Ninu Olaniyan, T and Quayson, A. (ed) African Literature, An Anthology of Criticism and Theory. UK: Blackwell Publishing.